Psalmu 116:1 Mo fẹ Oluwa, nitoriti o ti gbọ ohùn mi ati ẹbẹ mi. 116:2 Nitoriti o ti tẹ eti rẹ si mi, nitorina emi o kepè e niwọn igba ti mo ba wa laaye. 116:3 Irora iku yi mi ka, irora orun apadi si di mi mu mi: Mo ri wahala ati ibanuje. 116:4 Nigbana ni mo pè orukọ Oluwa; OLUWA, mo bẹ̀ ọ́, gbani là ọkàn mi. 116:5 Olore-ọfẹ li Oluwa, ati olododo; nitõtọ, alãnu li Ọlọrun wa. Daf 116:6 YCE - Oluwa pa òpe mọ́: a rẹ̀ mi silẹ, o si ràn mi lọwọ. 116:7 Pada si isimi rẹ, iwọ ọkàn mi; nítorí Yáhwè ti þe rere pelu re. Daf 116:8 YCE - Nitori iwọ ti gbà ọkàn mi lọwọ ikú, ati oju mi lọwọ omije, ati lọwọ mi ẹsẹ lati ja bo. 116:9 Emi o rìn niwaju Oluwa ni ilẹ awọn alãye. Daf 116:10 YCE - Emi gbagbọ́, nitorina li emi ṣe sọ: a pọ́n mi loju. Daf 116:11 YCE - Emi wi ni iyara mi pe, eke ni gbogbo enia. 116:12 Kili emi o san fun Oluwa nitori gbogbo ore rẹ si mi? 116:13 Emi o si mu ago igbala, emi o si kepè orukọ Oluwa. 116:14 Emi o san ẹjẹ mi fun Oluwa nisisiyi niwaju gbogbo awọn enia rẹ. 116:15 Iyebiye li oju Oluwa ni ikú awọn enia mimọ rẹ. 116:16 Oluwa, nitõtọ iranṣẹ rẹ li emi; iranṣẹ rẹ li emi, ati ọmọ rẹ iranṣẹbinrin: iwọ ti tú ìde mi. 116:17 Emi o ru ẹbọ ọpẹ si ọ, emi o si pè orúkæ Yáhwè. Daf 116:18 YCE - Emi o san ẹjẹ́ mi fun Oluwa nisisiyi niwaju gbogbo awọn enia rẹ̀. 116:19 Ni agbala ile Oluwa, lãrin rẹ, Jerusalemu. Yin OLUWA.